1 Chronicles 16:23-33


23 aKọrin sí Olúwa gbogbo ayé;
ẹ máa fi ìgbàlà rẹ̀ hàn láti ọjọ́ dé ọjọ́.
24Kéde ògo à rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
ohun ìyàlẹ́nu tí ó ṣe láàrín gbogbo ènìyàn.

25Nítorí títóbi ni Olúwa òun sì ni ìyìn yẹ Jùlọ;
òun ni kí a bẹ̀rù ju gbogbo àwọn Ọlọ́run lọ.
26Nítorí gbogbo àwọn ọlọ́run orílẹ̀-èdè jẹ́ àwọn òrìṣà,
ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
27Dídán àti ọláńlá ni ó wà níwájú rẹ̀;
agbára àti ayọ̀ ni ó wà ní ibi ibùgbé rẹ̀.

28Fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè,
ẹ fi ògo àti ipá fún Olúwa.
29Fún Olúwa ní ìyìn nítorí orúkọ rẹ̀;
gbé ọrẹ kí ẹ sì wá síwájú rẹ̀.
Sìn Olúwa nínú inú dídùn ìwà mímọ́ rẹ̀.
30Wárìrì níwájú rẹ̀, gbogbo ayé!
Ayé sì fi ìdí múlẹ̀; a kò sì le è ṣí i.

31Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn;
Jẹ́ kí wọn kí ó sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, pé “Olúwa jẹ ọba!”
32Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀;
Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀!
33Nígbà náà ni igi igbó yóò kọrin,
Wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa,
nítorí tí ó wá láti ṣèdájọ́ ayé.
Copyright information for YorBMYO